MUSAN FCE Abeokuta

MUSAN FCE Abeokuta

Share

A page for all music student at federal college of education abeokuta

08/05/2025

Watch this video to the end and share to everyone.

01/05/2025

ÀKÒRÍ: Ó DÁRA, Ó SÌ ṢE PÀTÀKÌ LÁTI MÁA KA BÍBÉLÌ NÍGBÀGBOGBO.

Ẹsẹ̀ Bíbélì: 2 Tímótì 3:16
Gbogbo ìwé-mímọ́ ni ó ní ìmísí Ọlọ́run, ó sì ní èrè fún ẹ̀kọ́, fún ìbáni-wí, fún ìtọ́ni àti ìkọ́ni nínú òdodo.

Bíbélì kìí ṣe ìwé kan ṣákálá tàbí ìwé yẹpẹrẹ - ó jẹ́ orísun ìtọ́nisọ́nà, ọgbọ́n, àti ìyípadà. Nínú 2 Tímótì 3:16 , a kà pé: “Gbogbo ìwé-mímọ́ ni ó ní ìmísí Ọlọ́run, ó sì ní èrè fún ẹ̀kọ́, fún ìbáni-wí, fún ìtọ́ni àti ìkọ́ni nínú òdodo.” Jẹ́ kí a ṣàwárí lára ìdí tí kíkà Bíbélì fi ṣe pàtàkì fún ìdàgbàsókè rẹ nípa ti ẹ̀mí àti nípa ti ara.

Ìdí Tí Kíkà Bíbélì fi ṣe pàtàkì ni wọ̀nyí?
1. Ìtọ́nisọ́nà: Bíbélì ń pèsè ìtọ́sọ́nà fún ìgbésí ayé wa, ó ń ràn wá lọ́wọ́ láti kojú àwọn ìpèníjà ìgbésí ayé àti ṣíṣe àwọn ìpinnu tó lọ́gbọ́n nínú (Òwe 3:5-6; Sáàmù 119:105).

2. Ọgbọ́n: Bíbélì jẹ́ orísun ọgbọ́n, ó ń fúnni ní ìjìnlẹ̀ òye nípa ìwà Ọlọ́run, ètò Rẹ̀ fún ìgbésí ayé wa, àti bí a ṣe lè gbé ìgbé ayé tó bọ̀wọ̀ fún Un (Jakọbu 1:5; Òwe 2:1-5).

3. Ìyípadà: Bíbélì ní agbára láti yí ìgbésí ayé wa padà, a máa ṣe ìrànlọ́wọ́ fún wa láti dàbí Kristi síi àti láti lè máa gbé ìgbé ayé tó ṣe àfihàn ìfẹ́ àti ìhùwàsí Rẹ̀ (Romu 12: 1-2; 2 Korinti 3: 18).

4. Ìtùnú: Bíbélì ń fúnni ní ìtùnú àti ìrètí ní àwọn àkókò tí ènìyàn bá ńla ìṣòro kọjá, a máa rán wa létí ìfẹ́ àti ìwàláàyè Ọlọ́run nínú ìgbésí ayé wa (Orin Dafidi 23; Matteu 11: 28-30).

5. Ìgbàlà: Bíbélì ni orísun ìgbàlà wa, o ńfi ètò Ọlọ́run hàn láti gba ẹ̀dá ènìyàn là kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àwọn àbájáde rẹ̀ (Johannu 3: 16; Romu 10: 9-10).

Olùfẹ́, inú Ọlọ́run máa ńdùn nígbà tí àwọn ènìyàn Rẹ̀ bá gba ọ̀rọ̀ Rẹ̀ gbọ́ tí wọ́n sì ń ṣe àṣàrò nínú ọrọ náà lóòrèkóòrè. A rí àpẹẹrẹ nínú májẹ̀mú titun bí àwọn ará Berea ṣe di àwọn ẹni tí a ń bọlá fún. A gbóríyìn fún wọn látàrí bí wọ́n ṣe fi ìtara gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run gbọ́ tí wọ́n sì ńṣe àyẹ̀wò àti àṣàrò rẹ̀ lójoojúmọ́ láti rí àrídájú àti láti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ àwọn ẹ̀kọ́ èyí tí Àpọsítélì Páùlù ńkọ́ni(Ìṣe Àwọn Àpọsítélì 17: 10-11).

Bákannáà, a rí àpẹẹrẹ mìíràn nínú ìwé mímọ́ nípa Jésù Kristì Olùgbàlà wa, òun pàápàá fẹ́ràn láti máa lo ìwé mímọ́ lóòrèkóòrè. Èyí farahàn nínú gbogbo àkọsílẹ̀ ìṣé ìránṣẹ́ Jésù Krístì. Ní pàtàkì jùlọ nínú ìwé Jòhánù 4:1-26, Jésù lo ìwé mímọ́ láti fi ìdánimọ̀ nípa ará rẹ̀ àti iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ hàn obìrin ará Samáríà, èyí jẹ́ àfihàn agbára Ọlọ́run láti yí ìgbésí ayé ènìyàn padà.

Síwájú síi Orin Dáfídì 119 ṣe àfihàn ìfẹ́ tí onísáàmù ní sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti bí ọ̀rọ̀ náà ṣe ṣe ìtọ́sọ́nà ìgbésí ayé rẹ̀. Matteu 4: 1-11 Ṣé àkọsílẹ̀ ìdáhùn Jésù sí ìdánwò, ní lílo ìwé mímọ́ láti borí àwọn ìkọlù àti àdánwò èṣù.
Nínú 2 Pétérù 1:3-8, a rí bí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣe ṣe pàtàkì, níní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run a máa ran ìgbàgbọ́ wa lọ́wọ́.

Kíka bíbélì rẹ ṣe pàtàkì fún ìdàgbàsókè nípa ti ẹ̀mí, ó jẹ́ ìtọ́sọ́nà, ọgbọ́n, ìyípadà, ìtùnú, àti ìgbàlà; nípasẹ̀ agbára ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, a lè ní ìrírí àjọṣepọ̀ tó jinlẹ̀ pẹ̀lú Kristì kí a sì gbé ìgbé ayé tó fi ìfẹ́ àti ìwà Rẹ̀ hàn.

Ẹ̀kọ́ Bíbélì kíkà síwájú síi:
Jòhánù 1:1-14: Ṣe àfihàn Jésù Kristì gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
Hébérù 4:12: Kọ́ ẹ̀kọ́ nípa agbára ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láti yí padà sí Ọlọ́run àti láti tún ìgbésí ayé wa ṣe.
Sáàmù 19:7-11: Ṣàyẹ̀wò ìmọrírì onísáàmù fún ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti ipa tí ọ̀rọ̀ náà kó nínú ìgbésí ayé rẹ̀.

Jẹ́ kí a jẹ́rìí sí àgbára Ọlọ́run nínú ìgbésí ayé wa pẹ̀lú àwọn àgbàṣẹ àdúrà wọ̀nyí:

1. Gbàdúrà fún ebi fún ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti ìfẹ́ láti máa káà àti láti máa ṣàṣàrò nínú rẹ̀ nígbàgbogbo.
2. Béèrè fún ìtọ́sọ́nà àti ọgbọ́n Ọlọ́run bí o tí ńka ọ̀rọ̀ náà tí o sì fi ńṣe ìwàhù
3. Sọ fún Olúwa wípé kò ṣe ìyípadà nínú ayé rẹ kí Ó sì sọ ọ dí ẹ̀dá titun nípasẹ̀ agbára tí ńbẹ nínú ọ̀rọ̀ Rẹ̀.
4. Gbàdúrà fún ìtùnú àti ìrètí nígbà tí ìṣòro bá dé, sọ fún Olúwa wípé k'Ó fún ọ ní agbára láti lè gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìlérí àti àwàláàyè Rẹ̀.
5. Béèrè fún ìgboyà àti ìrètí láti máa tan ìmọ́lẹ̀ Rẹ káàkiri nípasẹ wíwàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn àti nípa kíkó ipa rere ní agbègbè rẹ.

Bíbélì jẹ ìwé òfin àti ìlànà tí ó tóbi jùlọ tí Ọlọ́run fifún ìjọ Rẹ̀. Ó jẹ́ orísun ìgbàgbọ wa, ìpìlẹ̀ ìrètí wa, àti ìtọ́sọ́nà fún ìgbésí ayé wa.
Nítorí náà, olùfẹ́ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ìtọ́sọ́nà rẹ, àti àwọn ìlérí Rẹ̀ jẹ́ orísun ìrètí àti agbára rẹ.

Nípa ìtọ́ni àti ìdarí Ẹ̀mí Mímọ́ láfi kọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yìí láti ọwọ́ Ajíhìnrere Oluwaseun Samson, Olùdásílẹ̀ Yorùbá Gba Jésù Kristì Gbọ́.*

Tẹ ọ̀nà àsopọ̀ ìsàlẹ̀ yìí láti darapọ̀ mọ́ wa l'órí Facebook (clink the link below to follow us on Facebook) 👇

https://www.facebook.com/profile.php?id=100077387536475

05/03/2025

Have you seen this video? 👇

01/03/2025

Kò Sẹ́ni Tó Ní Ìdí Láti Yin Olúwa Àfi Ọkàn Alààyè

Ẹ̀yin ará nínú Kristi,
Lónìí, a óò máa kọ́ ẹ̀kọ́ lóríi kíni ó túnmọ̀ sí láti jẹ́ ọkàn alãye àti ìdí tí àwọn ẹ̀mí alãye nìkan ní ìdí láti yín Olúwa.

Kíni Ọkàn tàbí Ẹ̀mí Alààyè jẹ́?

Alààyè ọkàn ni ẹnìkan tí ó ti gba Jésù Kristì gẹ́gẹ́ bí Olúwa àti Olùgbàlà wọn, àti àwọn tí a ti tipasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ Ọlọ́run sọ di àtúnbí tàbí ẹ̀dá titun(Johannu 3: 3-6). Alààyè ọkàn ni a fihàn nípa ìfẹ́ wọn fún Ọlọ́run, ìgbọràn wọn sí Ọ̀rọ̀ Rẹ̀, àti ìfẹ́-inú wọn láti sìn ín lí ẹ̀mí àti lí òtítọ́.

Kíni Ẹ̀mí Alààyè Léè Ṣe (Ìdí Tí A Fi Dá Ọ Gẹ́gẹ́ Bí Alààyè Ọkàn 1)?
Gẹ́gẹ́bí ẹ̀mí alãye, o ní agbára láti:

- Yin Ọlọrun, kí o sì jọ́sìn Rẹ̀ (Orin Dafidi 103:1-5).
- Sin Ọlọ́run pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ (Deuteronomi 10: 12-13).
- Sọ̀rọ̀ ìhìn rere Jésù Kristì Olùgbàlà pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn (Mátíù 28:18-20).
- Gbé ìgbésí ayé ìgbọràn sí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run (Jòhánù 14:15).
- So èso fún ìjọba Ọlọ́run (Johannu 15: 1-8).

Kíni Ọkàn Alààyè Léè Yípadà (Ìdí Tí A Fi Dá Ọ Gẹ́gẹ́ Bí Alààyè Ọkàn 2)?
Gẹ́gẹ́bí ẹ̀mi alãye, o ní agbára láti:

- Ba gbogbo iṣẹ́ àti agbára okunkun jẹ́, kí o sì yí ìpinnu búburú wọ́n padà sí rere (1 Johannu 3: 8).
- Gba ìtúsílẹ̀ kúrò nínú ṣèkẹ́ṣẹkẹ̀ àti ìgbèkùn ẹ̀ṣẹ̀ (Romu 6: 17-18)
- Dáríjì àwọn ẹlòmíràn kí o sì gba ìdáríjì (Matteu 6: 14-15)
- Gbé ìgbé ayé ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá (1 Kọ́ríńtì 15:57)

Kí Ni Ọlọ́run Ǹretí Lọ́wọ́ Ọkàn Alààyè?
Àwọn ǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run ńretí lọ́wọ́ alààyè ọkàn:

- Fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn, ẹ̀mí àti èrò inú rẹ (Matteu 22:37-40).
- Ṣègbọnràn sí àwọn àṣẹ Rẹ̀ (Jòhánù 14:15).
- Máa sìn àwọn ẹlòmíràn nínú ìfẹ́ (Gálátíà 5:13-14).
- Jẹ́rìí sí oore Rẹ̀ (Orin Dafidi 96: 2-3).

Kíni Ó Ńyọrísí Ìparun Ayérayé?
Àwọn ǹkan wọ̀nyí a máa yọrí sí ìparun ayérayé

- Tí ènìyàn bá kọ ìfẹ́ àti ìgbàlà Ọlọrun (Johannu 3:36).
- Tí ènìyàn bá tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìgbọràn (Heberu 10: 26-27).
- Tí ènìyàn bá kùnà láti dáríjì àwọn ẹlòmíràn (Matteu 6: 14-15)
- Tí ènìyàn bá ńgbé ìgbésí ayé ìmọtara-ẹni nìkan àti ìgbéraga (Owe 16:18)

Jẹ́ kí a wo àpẹẹrẹ méjì láti inú ìtan-àkọọ́lẹ̀ inú ìwé mímọ́:

Ìtàn Dáníẹ́lì
Dáníẹ́lì, olóòótọ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run, kì í ṣe pásítọ̀ alákòókò kíkún, ṣùgbọ́n ó gbé ìgbésí ayé ìgbọràn àti ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Ọlọ́run. Ó kọ̀ láti ba ìgbàgbọ́ rẹ̀ jẹ́, pàápàá ní ojú ewu àti inúnibíni ( Danieli 1: 8-16; 3: 16-18, 6: 1-28 ). A gbóríyìn fún bí o ṣe jẹ́ olóòtító nípasẹ bí ọba ṣe dáa lọ́lá tí o sì gbéega sí ipò agbára àti ìyí.

Ìtàn Júdásì Ísíkáríọ́tù
Júdásì ẹ̀wẹ̀, ọ̀kan lára ​​àwọn àpọ́sítélì Jésù méjìlá, fara hàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọra àti ìmọtara-ẹni-nìkan ló sún un sí ìkọ̀kọ̀. Ó da Jésù fún ọgbọ̀n ẹyọ owó fàdákà, èyí yọrí sí dídá Jésù mọ́ àti bí wọ́n ṣe kàn án mọ́gi (Mátíù 26:14-16, 47-50). Iṣẹ́ àti ìwà Júdásì mú k'ó yọrí ìrìn àjò rẹ̀ sí ìparun (Iṣe Awọn Aposteli 1:18-19).

Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àti Ìwòye Síwájú síi:
Ya àkókò díẹ̀ sọ́tọ̀ láti ṣ'àṣàrò lórí àwọn ẹsẹ̀ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wọ̀nyí:

— Sáàmù 103:1-5 — Jòhánù 3:3-6 — Róòmù 6:17-18 — 1 Kọ́ríńtì 15:57

Béèrè àwọn ìbéèrè wọ̀nyí lọ́wọ́ ara rẹ:
1. Kíni ó túnmọ̀ sí láti jẹ́ ẹ̀mí alãye?
2. Báwo ni mo ṣe lè gbé ìgbé ayé ìgbọràn sí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run?
3. Kíni díẹ̀ nínú àwọn agbègbè nínú ìgbésí ayé mi níbití mo nílò láti dáríji àwọn ẹlòmíràn tàbí wá ìdáríjì?

Ronú Lórí Àwọn Òtítọ́ Ọ̀rọ̀ Ìyè Wọ̀nyí:
- Ọkàn alààyè dàbí àkójọpọ̀ àwọn tí ńfi ohun èlò orin oríṣiríṣi kọrin tó kún fún ìrètí àti ayọ̀, tí ń ṣeré ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run; ọkàn aṣákolọ, ìlú tí kò dún, orin tí kò dùn, ìdákẹ́jẹ́ẹ́ tí kò ní ìtumọ̀.”

- Ọkàn tó wà láàyè fún Kristì ń tan ìmọ́lẹ̀, ó sì ń kó ipa rere nínú ayé ọ̀pọ̀lọ̀pọ̀ ènìyàn, nígbàtí ọkàn tó gbádùn ayé àti ìfẹ́kùfẹ́ inú rẹ̀ paramọ́ bí òdòdó tí kò rí òòrùn láti tàn síi, àti omi láti mú-n tutù, nígbàtí ó ṣe, ẹ̀ka rẹ̀ rù, ó sì kú danù.

- Ẹ̀mí tó wà láàyè fún Kristì a máa jó nínú òjò oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run nígbàtí ọkàn aṣẹ́kolọ sinmi sínú ẹkún òun ìpahín keke.

Jẹ́ Kí A Jẹ́rìí Sí Ìfarahàn Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Nínú Ayé Wa Pẹ̀lú Àwọn Àgbàṣẹ Ádùrá Wọ̀nyí:

1. Olúwa, ràn mí lọ́wọ́ láti gbé bí ẹ̀mí t’ó ḿbe, t’ó gbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Rẹ, tí ó sì kún fún ìfẹ́ Rẹ.
2. Bàbá mi àti Ọlọ́run mi, fún mi ní ìgboyà láti pín ìhìnrere pẹ̀lú àwọn ẹlòmíràn àti láti sìn Ọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
3. Ẹ̀mí Mímọ́, ràn mí lọ́wọ́ láti dáríji àwọn ẹlòmíràn àti láti rí ìdáríjì gbà, kí èmi kì ó lè gbé ìgbé ayé òmìnira àti ayọ̀.
4. Olúwa fí àbò Rẹ bò mí lọ́wọ́ ìdánwò láti bá ìgbàgbọ́ mi jẹ́ àti láti gbé ìgbé ayé ìmọtara-ẹni-nìkan àti ìgbéraga.
5. Ẹ̀mí Mímọ́, ní gbogbo ìgbà tí O bá ńbá mi sọ̀rọ̀, fún mi ní etí ìgbọ́ àti àyà ìgbàṣe , kí nlè so èso fún ìjọba Rẹ, kí ayé mi lè fi ògo àti ọlá fún orúkọ Rẹ.

Olùfẹ́ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ìtọ́sọ́nà rẹ, àti àwọn ìlérí Rẹ̀ jẹ́ orísun ìrètí àti agbára rẹ.

Nípa Ìmísí Àti Ìdarí Ẹ̀mi Mímọ́ Lafi Kọ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Yìí Láti Ọwọ́ Ajíhìnrere. Sefunsam Chord.

15/02/2025

A Life-Changing Message. Read, Like, Comment, and Share with Your Loved Ones.

10/02/2023

10:02:2023
Àkòrí: ǸJẸ́ O NÍ ÌBẸ̀RÙ ỌLỌ́RUN?
APÁ KEJÌ.

Ẹsẹ̀ Bíbélì: Filipi 2:12-13 FILIPI
Nítorínà ẹ̀ǹyin olùfẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ǹyin ti ńgbọ́ran nígbàgbogbo, kì ìse nígbàtí mo wà lọ́dọ̀ nyìn nìkan, ṣùgbọ́n pàápàá nísisìyí tí èmi kò sí, ẹ mã ṣiṣẹ́ ìgbàlà nyìn yọrí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì, nítorípé Ọlọ́run ni nṣiṣẹ́ nínú nyín, láti fẹ́ àti láti ṣiṣẹ́ fún ìfẹ́ inú rere Rẹ̀.

Gẹ́gẹ́bí onígbàgbọ́, ǹjẹ́ ìwọ́ ńpa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mọ́ ní oókan àyà rẹ lójoojúmó àbí níse ni o máa ń taá danú ní wákàtí tí Ọlọ́run bá fẹ́ kí o jẹ́wọ́ títóbi Rẹ̀ níwájú ọ̀pọ̀ ènìyàn? Títóbi agbára Ọlọ́run jẹ́ ohun tí a gbọ́dọ̀ máa wárí fún gẹ́gẹ́ bí ọmọ lẹ́yìn Kristi kí a sì gba ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láàyè láti máa tẹrí ọkàn wa ba lòdì sí ìṣe ti ara èyí tí ó lè fẹ́ jẹ́ kí a lòdì sí ìtọ́ni Ẹ̀mí Mímọ́.

Àìmọye onígbàgbọ́ ló jẹ́ wípé wọn a máa f'ara hàn nílé ìjọsìn gẹ́gẹ́bí ẹni mímọ jùlọ sùgbọ́n tó jẹ́ wípé ìgbésí ayé wọn kò fi ọlá fún Ọlọ́run rárá. Ọ̀pọ̀ ni kìí ṣe àgbèrè tàbí panṣágà tàbí ja olè tàbí mu ọtí, sùgbọ́n t'ó bá jẹ ìbínú sódì, odì yíyàn, èké ṣíṣe, ìlara àti lílo àwọn ọ̀rọ̀ èyí tí àwọn t'ayé máa ń lò, bàbá ni wọ́n.

Gbogbo wa náà la kúkú mọ́ wípé ayé òlàjú làwá, ẹ̀rọ aláàgbéká tí a ńlò ní ayé òde òní ti la ọ̀pọ̀ lójú sódì sí òtítọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti wípé àwon ohun tí ó ń lọ lórí afẹ́fẹ́ èyí tí ọ́pọ́ ènìyàn fẹ́ràn láti máa wò àti láti máa fi etí gbọ́ tí mú kí ìbẹrù Ọlọ́run kúrò ní inú ọkàn wọn.

Bíbélì wípé, ẹ kọjú ìjà sí èṣù oun yíò sì sa fún yín, kaka ki ọ̀pọ̀ ènìyàn kọjú ìjà sí àwọn ohun náà èyí tí yíò mu kí ìbẹrù Ọlọ́run kúrò nínú ayé wọn, níse ni wọ́n gbá sátánì móra pẹ́kípẹ́kí. Ìgbàlà ọkàn wa ṣe iyebíye níwájú Olúwa, sùgbọ́n ó ṣeéṣe kí a sọ ìgbàlà ọkàn wa nù tí a bá kò láti máa níi lọ́kàn nínú ohun gbogbo ti a bá nṣe wipe ojú Ọlọ́run ńbẹ lara wa tí a kò sí bẹ̀rù Olúwa.

ÀDÚRÀ
Bàbá mi àti Ọlọ́run mi, rán mí lọwọ, ohun ayé ma jẹ kó gbámi kúrò lọ́dọ̀ Rẹ, jẹ́ kí nlé máa ṣiṣẹ́ ìgbàlà mí pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì, jẹ kí nlé máa gbà ìtọ́ni àti ìdarí Ẹ̀mí Mímọ́ Rẹ lójoojúmó kí ẹsẹ mi máṣe yẹ. Àmín!

15/01/2023

Jesus Christ is the only way to eternal life, He is the truth and life eternal while every other ways lead to damnation.

Repent from your evil ways today and give your life to Him by confessing Him as your personal Lord and Savior and tell Him to baptize you with the Holy Ghost and Fire so that you can start having access to daily interaction with Him which brings about eternal recognition in the kingdom of God.

If you are ready to give your life to Jesus Christ so that you can be save from the destruction that is coming upon every souls that reject and condemn this truth, forward a message to Evangelist Sefunsam Chord @ [email protected], stating that you want to give your life to Jesus Christ.

I will pray for you and also review to you the secret to living a fulfilling life in Jesus Christ which will actually help you to dislodge yourself from all kinds of ungodly associations or demonic activities that you have once find yourself or you belonged before now and total freedom shall be ascertained.

15/01/2023
15/01/2023

AKORI: DURO T**I LAILAI.

Ese Oro Olorun: Psalm 125:1
Awon ti o gbẹkẹle Oluwa yio dabi òke Sioni, ti a kò le ṣi ni idi, bikoṣepe o duro lailai.

Aku odun, aku iyedun. Bi Jesu Kristi ba fa bibo Re seyin a o se opo odun laye ati ni aye rere.

Olufe, wo, maje ki enikeni ki otan o je, katowi katofo odun 2023 yìí náà a lo sopin. Ojo nlo, akoko koduro denikeni. Sugbon ohun kan ni mofe ki o mo daju, ohun náà sini wipe ninu odun yìí afefe yio fe, iji yioja, sùgbón ki yio se owo odi si o lara. Ohun kohun yowu ki osele ni inu aye, Olórun ti seto ohun gbogbo daradara eyi t'oje wipe yio mu ayo ati inu didun pelu iserere ba awon ti oba gbeke won le-e.

Ese oro Olorun fun ojo oni sowipe: awon ti o gbẹkẹle Oluwa yio dabi òke Sioni, ti a kò le ṣi ni idi, bikoṣepe o duro lailai.

Bi oba gbeke re le Oluwa, oro Olorun so wipe dipo ki asi o ni'di, nise ni wa a duro t**i lailai. Iroyin ayo nla ni eyi je nitoripe ooni rin irin ajo odun yìí lalaini olugbeja eyi ti yio gba ija re ja ti yio si fi ese re mule bi oba gbe okan re le-e.
Kiwani otunmo si lati gbekele Oluwa? Ao maa ye ñkan wonyi wo lati ola lo. Leekan si, aku oriire asi ku ajaye bosi inu odun titun. Odun yi a tuwa lara ni oruko Jesu Kristi. Amin!

ADURA
Babami ati Olórun mi, alágbára ti mo gboju le, oseun fun owo agbara Re eyi ti ofi dimi mu lati ibere odun 2022 t**i de ibere odun 2023. Mo gbe oju mi soke si o ninu odun yi, Oluwa mu oro Re se simi lara. Bi mo se n pin-nu lati gbokan le o ninu odun yi Baba mi bami rin irin ajo náà, mumi duro sinsin, fokan mi bale kuro ninu ewu gbogbo, ògo ni fun oruko Re, ni oruko Jesu Kristi ni mo gbadura. Amin!

Want your school to be the top-listed School/college in Abeokuta?

Click here to claim your Sponsored Listing.

Location

Category

Website

Address


Federal College Of Education, Oseile, Abeokuta. Nigeria �
Abeokuta
234039