18/06/2026
ÈDÈ ÌPERÍ YORÙBÁ/YORÙBÁ LEXICON
Pípọ́n ẹyinjú: Ẹyinjú yíyún tí ó sì pọ́n.
Iridocyclitis: Inflammation of the iris and ciliary body of the eye.
© English-Yoruba Glossary of HIV, AIDS and Ebola-related terms
17/06/2026
PÀTÀKÌ ORIN ÌRẸMỌLẸ́KÚN/ ESSENCE OF LULLABY
Orin Ìrẹmọlẹ́kún jẹ́ ọ̀kan gbòógì nínú àwọn ewì àtẹnudẹ́nu tí à ń kọ fún ọmọdé láti rẹ̀ ẹ́ dákẹ́ bí ó bá ń sunkún tàbí láti mú kí ó sùn wọra ní ìrọ̀rùn ní ilẹ̀ Yorùbá. Àwọn obìnrin/abiyamọ ló sábà máa ń kọ ẹ̀yà ewì yìí. Lára àwọn ohun tí ó máa ń hànde nínú orin Ìrẹmọlẹ́kún ni ìfẹ́, ìwúre, ẹ̀kọ́ àti oríkì.
Lullaby is one of the fundamental forms of oral poetry sung to children to soothe them when they cry or to help them fall into a peaceful sleep with ease in Yorùbá land. The poetry is mostly used by women/mothers Some of the key elements found in Yoruba lullabies include love, prayers, moral teachings, and eulogy.
📷Pinterest
14/06/2026
IPA PÀTÀKÌ ÌṢẸ́GUN ÌBÍLẸ̀ LÁWÙJỌ WA
Ọyẹ́ mú o kò funfun
Ìrí sẹ̀ o kò jọ̀lọ̀
Oníṣègùn ni yóò fowó rẹ mùkọ.
Kókó àṣàyàn ọ̀rọ̀ yìí tẹnumọ́ pàtàkì àlàáfíà àti ìlera, pàápàá jùlọ ipa àyípadà ojú ọjọ́ lórí ẹ̀dá . Ìlànà gbòógì tí Yorùbá fi ń ṣètò ìlera ni ìṣẹ́gun ìbílẹ̀. Ipò ìṣẹ́gun ìbílẹ̀ wà ní àwùjọ Yorùbá kò ṣe é fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn rárá. Ìṣẹ́gun ìbílẹ̀ jẹ́ ẹ̀ka àwùjọ tí ó ṣe ìṣelọ́jọ̀ ayé ẹ̀dá, ó ń pèsè ààbò, ó ń mójútó ètò ìlera, ó ń ṣètò arẹmọ bẹ́ẹ̀ náà ló ń dènà àìsàn àti ewu gbogbo.
THE VITAL ROLE OF TRADITIONAL MEDICINE IN OUR SOCIETY
The Harmattan brings no luster to your skin
Morning dew cannot revive your glow within
All your earnings will go towards doctor's fees
The importance of vitality and health is underscored in this witty saying, highlighting the significance of traditional medicine in Yorùbá society. Traditional medicine plays a vital role in preserving human life, offering protection, and promoting overall health, fertility, and well-being, while also preventing diseases and mitigating associated risks, thereby underscoring its invaluable contribution to the society.
12/06/2026
ÀÀFIN ỌLỌ́WỌ̀/ ỌLỌ́WỌ̀ PALACE
Ààfin Ọlọ́wọ̀ àtijọ́ ní ìlú Ọ̀wọ̀ ní Ìpínlẹ̀ Oǹdó ní ìwádìí sọ pé ó jẹ́ ààfin tó tóbi jù ní ilẹ̀ Adúláwọ̀. Ẹgbẹ̀rún ọdún sẹ́yìn ó lé díẹ̀ ni wọ́n kọ́ ààfin náà tí yàrá ibẹ̀ sì tó ẹgbẹ̀rún, àwọn ibùdó ìsọlọ́jọ iṣẹ́ ọ̀nà àti ọjà náà wà níbẹ̀. Ìjọba àpapọ̀ orílẹ̀èdè Nàìjíríà kéde ààfin náà gẹ́gẹ́ bí ohun ìrántí Orílẹ̀èdè ní ọdún 2000.
Ancient Ọ̀wọ̀ palace is reported to be the largest palace in Africa, and it is located on 180 acres of land. The palace was built almost over 1,000 years ago and features over 1,000 rooms, museums and markets. The federal government of Nigeria declared the palace a national monument in 2000.
09/06/2026
YORÙBÁ PUBLIC LIBRARY
Yorùbá Public Library ṣètò Láíbìrì ajẹmọ́dííjìtì láti fi ìmọ̀ ẹ̀rọ ṣe àwọn ohun àjogúnbá àti àṣà lọ́jọ́ kí àwọn nǹkan wọ̀nyí lè wá ní tọ́rọ́-fọ́n-kálé àti ní àrọ́wọ́tó fún lílò lásìkò-kásìkò pẹ̀lú ìrọ̀rùn jọjọ.
Yoruba Public Library established a digital library to use technology in preserving cultural heritage materials and traditions, ensuring that these resources are available online and easily accessible for use at any time with great convenience.
07/06/2026
ỌDÚN AJÍLÁÀLÁ Ọ̀ṢỌ́/FESTIVAL
Ọdún Ajíláàlá Ọ̀ṣọ́ . jẹ́ èyí tí ó làmìlaka nínú àwọn ayẹyẹ ajẹmáṣà tí ó máa ń wáyé ní ọjọ́ kẹtà ọdún Iléyá ní ìlú Ẹdẹ, ó jẹ́ ayẹyẹ tí ó mú kí àwọn ọmọ ìlú péjú-pésẹ̀ láti ṣe àyẹ́sí Tìmì ìlú Ẹdẹ, èyí tí ó ń mú kí gbogbo èèyàn parapọ̀ láti fìmọ̀ṣọ̀kan
The Ede Ajilẹ́là Ọ̀só Festival is a colourful annual cultural celebration held in the town. It takes place on the third day after Eid al-Kabir (Iléyà) and serves as a homecoming event that honours and celebrates the Timi of Edeland, bringing indigenes together in unity and festivity.
📷 Osunmetro
06/06/2026
ÌPÁPÁNU ÌBÍLẸ̀ YORÙBÁ/YORÙBÁ INDIGENOUS SNACKS
Àádùn jẹ́ ìpàpánu Ìbílẹ̀ aládùn tí ó gbájúmọ́ ní ilẹ̀ Yorùbá. Àádùn túmọ̀ sí ohùn tí ó ládùn, ó wà lára èròjà tí ó wọ̀pọ̀ fún ìwúre ni ayẹyẹ bí ìgbéyàwó àti ìsọmọlórúkọ. Àwọn èròjà tí wọ́n fi ń ṣe àádùn ni àgbàdo yíyan lílọ̀, epo àti èròjà amọ́bẹ̀dùn
Àádùn is an indigenous street snack popular among the Yorùbás. The name àádùn means sweetness and it is also commonly used for prayers weddings and naming ceremonies. It is made from a combination of roasted corn flour, palm oil and spices.
📷9jafoodie
yorubapubliclibrary
03/06/2026
ÈDÈ ÌPERÍ YORÙBÁ/YORÙBÁ LEXICON
Àìsàn
adánigúnlẹ̀: ìdágúnlẹ̀ látara àárẹ̀ tàbí ogbó.
Bedridden: Confined to bed by sickness or old
age.
01/06/2026
IBÙDÓ OGUN OROKE EWO /OROKE EWO WAR CENTRE
Ibùdó Ogun Orókè Ewo wà nítòsí Ilúpéjú Èkìtì, wọ́n jábọ́ pé pé ibùdó náà jẹ́ ibùdó ogun olókìkí tí ó wáyé láàárín àwọn ológun láti Ìlọrin ti Alí ṣáájú ogun àti ìlú Egòsì ti Oloseru ṣáájú. Ìtàn sọ pé àwọn ọmọ ìlú Egòsì dán oògùn wo tí wọ́n sì sọ àga àti igbá oògùn Àlí di òkúta tí a mọ̀ sí òdìdì-mọdẹ̀. Wọ́n sọ ìlú bẹ̀m̀bẹ̀ rẹ̀ di òkúta -Ojongbede, tí wọ́n sì sọ ràkúnmí rẹ̀ di igi osè, gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ni wọ́n ṣe lọ́jọ́ ní ibùdó yìí.
Oroke Ewo centre is located in Ilupeju Èkìtì and it is reported to be a sure of a popular war between warriors from Ìlọrin led by Ali and Egosi kingdom led by Oloseru. It was reported that Egosi people displayed magical powers and turned warlord Ali and his chair and calabash of charms into stones known as òdìdì-mọdẹ̀. The bembe drum was also turned to stone -Ojongbede while Ali's horse was turned into an ose tree, all of which are preserved at the centre.
©Ọ̀gbẹ́ni Babátúndé Fájuyì
📷Ida Ilupeju Ekiti Development Association
29/05/2026
OJÚDE ỌBA
Ojúde Ọba jẹ́ ọdún gbòógì ní ilẹ̀ Yorùbá pàápàá jù lọ láàárín àwọn Ìjẹ̀bú ní Ìpínlẹ̀ Ògùn, ọdọọdún ní ọjọ́ kẹtà Iléya ló máa ń wáyé. Lára àwọn ètò tí ó sódo sínú ọdún náà ni ìmúra onírúurú ẹgbẹ́, wọ́n yóò ṣe ìdíje regberegbe, ijó ìbílẹ̀ àti ìjúbá sí Àwùjalẹ̀. Ayẹyẹ náà máa ṣàfihàn ìṣọ̀kan, àjogúnbá, àṣà àti ìṣe àwọn Ìjẹ̀bú, èyí sì ń máa ń fa ọkàn àwọn akópa àti àlejò káríayé. Oní ni ọdún ojúde Ọba ọdún yìí.
Ojúde Ọba is a significant festival in Yorùbá land particularly by the Ìjẹ̀bús in Ògùn State. It is held annually two days after Eid-El-Kabir. The festival features colorful parades by different age groups competing for the best dressing, horse-riding, traditional dances, and homage paid by over 100 age-grade groups to the Awujale. The event showcases the unity, heritage, and traditions of the Ijebu people, attracting participants and visitors from across globe. Today is this year's Ojude Ọba's festival edition.